We Are The Charleans

International News - A Yoruba Perspective

From BBC


Ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Oyo bẹ̀rẹ̀ ní pẹrẹu
Ní nǹkan bíi aago mẹ́sàn-án òwúrò ọjọ́ Àbámẹ́ta, ọjọ́ Kẹtàdínlọ́gbgọ̀n, oṣù Kẹrin , ọdún 2024 ni ètò ìdìbò náà gbérasọ.

Mọ̀ nípa ẹgbẹ́ kan tó wà fún àwọn obìnrin tí kò fẹ́ l'ọ́mọ láyé
Ileeṣẹ BBC ba awọn obinrin to jẹ ọmọ ẹgbẹ Bristol Childfree Women sọrọ, wọn si salaye idi ti wọn ri ti wọn fi pinnu igbesẹ yii.

Aláboyún wà lára èèyàn tó ti pàdánù ẹ̀mí níbi ìṣẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná ní Rivers
Lasiko ti a n kọ iroyin yii, ko ti i sẹni to mọ iye eeyan to ku tabi farapa ninu iṣẹlẹ naa.

Yahaya Bello pe Alága EFCC lẹ́jọ́, ó ló tàpá sí àṣẹ kóòtù lórí ọ̀rọ̀ oun
Ẹsun ti Yahaya Bello n ka si Alaga EFCC lẹsẹ ni pe ile-ẹjọ ti paṣẹ fun un tẹlẹ pe ki wọn ma ti i gbiyanju lati mu oun rara.

Ṣé bí adẹrìn-ínpòṣónú Layi Wasabi ṣe mú lẹ́nu ló láyà tó?
Layi Wasabi darapọ̀ mọ́ BBC News Yorùbá lórí ètò 'Só o láyà' tọ̀tẹ̀ yìí lati mọ̀ bí Yorùbá rẹ̀ ṣe dáńtọ́ tó.

Òní lónìí ń jẹ́ ní ìpínlẹ̀ Oyo bí ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ yóò ṣe gbérasọ
O kere tan, awọn ẹṣọ eleto aabo bii ẹgbẹrun mẹẹdogun ni ajọ naa ti gba lati mojuto eto idibo naa, bakan naa si ni ajọ OYSIEC ti fi iroyin lede nipa igbanisiṣẹ awọn oṣiṣẹ eleto idibo bii ẹgbẹrun lọna ogoji ti yoo ṣe atọkun eto idibo naa jakejado ipinlẹ Ọyọ.

Bàbá mi Ogunjimi ti máa ń fi gbogbo ìgbà múra sílẹ̀ de ikú- Ismailia ọmọ olóògbé
Ismaila ni "baba mi Ganiyu Akinpelu jẹ eeyan takuntakun ninu ẹgbẹ osere tiata ati ninu ilu.''

Ìjọba yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní wó àwọn ilé tó wà lójú ọ̀nà mọ́rosẹ̀ Eko sí Calabar tí iṣẹ́ ń lọ lórí rẹ̀
Alakooso naa rọ gbogbo awọn tijọba ti sami sile wọn lati wo lulẹ, pe ki wọn tete lọ si ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Eko, lati pari eto gbogbo to yẹ.

Ilé alájà dàwó lu òṣìṣẹ́ márùndínlógún ní Kano
Ko tii si ẹni le sọ iye awọn eeyan ti wahala naa ṣe lọṣẹ.

Oyún oṣù méje ààbọ̀, tí Dókítà gbé jáde nínú ìyá rẹ̀ ní Gaza, ti jáde láyé
Ẹlẹmi gba ẹmi ọmọ jojolo naa ni Ọjọbọ ana, ti wọn si ti sin i si ẹgbẹ iya rẹ ẹni ti wọn fi orukọ rẹ sọ ọ.

Wo pàtàkì iṣan tó ń ṣiṣẹ́ bíi ọkàn, mú kí èèyàn fẹsẹ̀ méjì rìn, ó tún ń mú kí ẹ̀jẹ̀ ṣàn lára
Dokita Carles Pedret, akọṣẹmọṣẹ lati ileewe to n ri si ilera nipa ere idaraya ni Yunifasiti Barcelona ni iṣan Soleus nilo lati maa ṣiṣẹ deede keeyan le wa lalaafia ara.

Àgbàrá òjò gbé èèyàn 150 lọ, 51,000 míì di aláìnílélórí
Olugbe agbegbe Siha ni ariwa Tanzania sọ fun BBC pe ile oun ti dawo, oun si ti wa ni korofo bayii.

Àwọn gómìnà lápá Àríwá lọ Amẹ́ríkà láti wá ojútùú sí ààbò tó mẹ́hẹ, àbọ̀ wọn rèé
Awọn gomina lapa ariwa ni awọn ti ri awọn aṣiri kan to ju ti tẹlẹ lọ, eyi tawọn le fi koju iṣoro aabo to mẹhẹ naa.

Kí ló dé tí wàhálà bẹ̀rẹ̀ bí Togo ṣe fẹ́ kúrò nílànà òṣèlú ààrẹ sí ìṣèjọba ẹlẹ́kùnjẹkùn?
Atunṣe iwe ofin ni ọdun 2019 fi aye gba Aarẹ Gnassingbe lati jade dupo, eyi to fun ni anfani lati wa nipo títi wọ ọdun 2030.

Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba Eko buwọ́lu ₦70,000 bíi owó oṣù òṣìṣẹ́ tó kéré jùlọ?
Atẹjade kan ti Kmisana feto iroyin nipinlẹ Eko fisita loju opo Twitter rẹ, ni ko si ohun to jọ afikun owo osu osisẹ, awọn araalu kan ṣi gomina naa gbọ ni.

Igbákejì Gómìnà tẹ́lẹ̀rí Agboola Ajayi jáwé olúborí nínú ètò ìdìbò abẹ́lé PDP l'Ondo
Alaga igbimọ ẹlẹni meje to dari eto idibo naa nipinlẹ Ondo ti i ṣe Igbakeji Gomina Ipinlẹ Bayelsa, Sẹnẹtọ Ewhrudjakpo Oborawhartevwo lo kede Ajayi gẹgẹ bi ẹni to bori.

Ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ kéde pé owó òṣù tí ìjọba ń san fún aya ààrẹ àti aya igbákejì ààrẹ lòdi sófin
Igbimọ adajọ ẹlẹni meje ti adajọ Gertrude Torkonoo dari rẹ fidi rẹ mulẹ pe ipo aya aarẹ ati aya igbakeji aarẹ kii ṣe ipo ọfiisi ijọba to tọ si owo oṣu gbigba.

Ọwọ́ ti tẹ mẹ́tàlá nínú àwọn ẹlẹ́wọ̀n tó sá lọ́gbà ẹ̀wọ̀n Suleja - Mínísítà
Igbakeji adari ileeṣẹ ọgba ẹwọn lagbegbe FCT, AS Duza lo fidi iroyin naa mulẹ ninu atẹjade kan.

Kí ni El Niño àti La Niña, kí ní àjọṣepọ̀ wọn pẹ̀lú ojú ọjọ́?
El Niño ati La Niña, mejeeji yii jẹ ohun pataki si ayipada oju-ọjọ lagbaye.

Ẹ má kó oúnjẹ 5000 tí mo pín lọ sílé yín, àwọn mẹ̀kúnnù tó nílò rẹ̀ ni kí ẹ pín fún - Sanwo-Olu kìlọ̀
Ijọba Eko ni awọn eeyan ijọba ibilẹ ogun ati tawọn onidagbasoke (LCDA) mẹtadinlogoji to wa l’Ekoo ni yoo janfaani ounjẹ naa.

Bàbá mi kò lórúkọ́ àmọ́ èmi ti fòpin sí óṣèlú ‘ta a ni baba rẹ’ nipinlẹ Ọyọ - Ṣeyi Makinde
Ṣeyi Makinde ṣalaye pe igba kan ti wa ri nipinlẹ Ọyọ, to jẹ ta a ni baba tiẹ nilẹ yii ni wọn fi n se oṣelu.

Ọwọ́ ti tẹ mẹ́tàlá nínú àwọn ẹlẹ́wọ̀n tó sá lọ́gbà ẹ̀wọ̀n Suleja - Mínísítà
Igbakeji adari ileeṣẹ ọgba ẹwọn lagbegbe FCT, AS Duza lo fidi iroyin naa mulẹ ninu atẹjade kan.

Egypt ni Orunmila ti rìn wá, kìí ṣe Ile Ife, Ife kọ́ ni olùdáyé - Babaláwo
BBC Yorùbá bá Baba awo Obafemi Makinde sọ̀rọ̀ lórí Àtúpalẹ̀ ẹ̀sìn ifá, ẹni tó ṣàlàyé bí Orunmila ti ṣẹ̀ wá láti ilẹ̀ Egpty yàtọ̀ sí ilú Ile Ife tí ọ̀pọ̀ èèyàn rò pé ó jẹ́ Olùdáyé.

Àlàyé rèé lórí ìdí tí Amẹ́ríkà ṣe fẹ́ fòfin de TikTok
Aarẹ Amẹrika tẹlẹ ri, Donald Trump naa gbiyanju lọdun 2020 lati fofin de TikTok lasiko ijọba rẹ.

Mo ti bá olóòtú fíìmù lòpọ̀ rí, kí n lè kópa nínú sinimá rẹ̀ – Seun Sean Jimoh
Seun Sean Jimoh bo tilẹ jẹ pe iṣẹlẹ naa ti kuregbe-kuregbe, o ni o ṣi maa n ba oun ninu jẹ titi di oni yii.

Wàhálà míí tún bá Emefiele, EFCC ní odidi N18.9bn ló fi tẹ owó péréte N684.5m, òun yóò ba ṣe ẹjọ́ míì
Ọgbọnjọ oṣu Kẹrin ọdun yii ni Emefiele yoo foju ba ile ẹjọ niwaju adajọ Maryann Anenih ile ẹjọ giga ijọba apapọ niluu Abuja.

Ìdílé mùsùlùmí ẹlẹ́ni méje na ọmọbìnrin tó lọ ṣọ́ọ́ṣì ní pàsán ọgọ́rùn-ún, wọ́n dèrò àtìmọ́lé
Ọmọdebinrin kan ẹni ọdun mejidinlogun, Shakira Naula ni fidio naa se afihan rẹ pe Jaberi ati awọn eeyan kan n to ẹgba to to ọgọrun si nidi.

Multichoice kéde àfikún owó orí DStv, GOtv
Oṣu diẹ sẹyin ni afikun ṣi de ba owo ti awọn onibara n san fun mohunmaworan agbelewo DStv ati GOtv.

Ìjọba Nàìjíríà gbẹ́sẹ̀ lé iléeṣẹ́ bàlúù Dana Air
Lọjọ Iṣẹgun ni baluu Dana Air kan to fẹ ba ni papakọ ofurufu MMA ni ilu Eko yọ gẹrẹ kuro loju opo baluu ni papakọ ofurufu naa

Àwọn àgbébọn kan fẹ́ jọ́wọ́ ohun ìjà wọn fún ìjọba láti kẹ̀yìn síwà ọ̀daràn – Ribadu
Ni ijọba ibilẹ Kankara, iṣoro eto abo tun ti n pada sawọn agbegbe kan nibẹ.

Bàbá, ọmọ àti aládùúgbò kú sí ṣálángá ni Kano
Ẹrọ ibanisọrọ Mallam Danjuma lo ṣeṣi ja si ṣalanga oniho naa nigba ti baba yii wa ninu ile igbọnsẹ ọhun, o si gbiyanju lati wọnu rẹ lọọ mu un.

Ọba Yoruba lórílẹ̀èdè Togo, Abdlkareem Afolabi Amon-lòkò wàjà
Wọn ti ṣeto isinku ori ade naa ni ilana ẹsin Musulumi.

Ọlọ́pàá yìnbọn pa ẹ̀gbọ́n tó wá bá àbúrò rẹ̀ yọ àyọ̀ ìkẹ́kọ̀jáde ní fásitì LAUTECH, èèyàn méjì míì farapa
Iroyin ni ọkan lara awọn oṣiṣẹ SARS, ti ijọba fopin si lọdun meji sẹyin ni ọlọpaa to yinbọ naa, eyii to ṣekupa agunbanirọ ti wọn pe orukọ rẹ ni Iyanda Damilola.

"Ẹ̀rù máa ń bà wá tẹ́lẹ̀ láti farahàn bíi oníṣẹ̀ṣe l‘Oyo, Ọba Adeyemi ló tì wá lẹ́yìn tí ìṣẹ̀ṣe kò fi di àtẹ̀mẹ́rẹ̀"
BBC Yorùbá wà ní ìlú Oyo fún ìrántí Aláàfin Lamidi Olayiwola Adeyemi tó wàjà lọ́dún méjì sẹ́yìn láti fojú ṣe mẹ́rin àwọn ètò ìrántí fún ọba tó dí olóògbé náà.

Remi Tinubu ló ń bá mi wá ọ̀nà àbáyọ sọ́pọ̀ ìpèníjà tó ń kojú mi - Ademola Adeleke
Gomina Ademola Adeleke sọ ọrọ yii lasiko ti aya aarẹ orilẹede Naijiria, Oluremi Tinubu, ṣe abẹwo si ipinlẹ Ọṣun lati si awọn akanse isẹ kan.





We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always



This Section Can Accommodate Your Adverts





Charleans In Celebration Mode

We have put an assorted mix of pics here for your enjoyment. We are always hungry for more - so if you have taken or have access to some pics remotely related to our issue, please do not hesitate to send them to the web admin team

SCOBA PARTNERS

corporates and enterprise businesses we have the pleasure to connect with.