We Are The Charleans

International News - A Yoruba Perspective

From BBC


Ìṣesí wọn nílé aṣòfin àgbà dà bí tilé ẹgbẹ́ awo - Natasha Akpoti
Natasha sapejuwe ile asofin agba bẹẹ lasiko to n ba BBC sọrọ lori awọn idojukọ rẹ nile asofin agba.

Israel rọ òjò àdó olóró sí Gaza lásìkò tí wọ́n ń jí sààrì, èèyàn 330 dèrò ọ̀run
Aṣoju ijọba Israel si ajọ UN, Danny Danon, sọ pe "A ko ni fi oju aanu wo awọn ọta wa."

Wo àwọn ẹ̀sùn tí Ilé aṣòfin Rivers fi kan Gómìnà àti igbákejì rẹ̀ láti yọ wọ́n nípò
Àwọn aṣòfin mẹ́rindínlọ́gbọ̀n ni wọ́n ń fẹ̀sùn kan gómìnà àti igbákejì rẹ̀ ọ̀hún nínú ìwé àkọránṣẹ́ kan tí wọ́n fi ṣọwọ́ sí olórí ilé aṣòfin, Martin Amaewhule lọ́jọ́ Ajé.

'Afurasí tó pa Mojisola Awesu ti láwọn ẹ̀sùn ọ̀daràn tẹ́lẹ̀ lọ́dọ̀ ọlọ́pàá, ìgbà àkọ́kọ́ rẹ̀ kọ́ yìí'
Nibi igbẹjọ naa, ni ile ẹjọ giga ipinlẹ Kwara to wa ni Ilorin, ni awọn ẹlẹrii ti n sọrọ lori ohun ti wọn mọ lori iku ọmọbinrin naa.

Sowore, àwọn agbẹjọ́rò tẹ̀lé àgùnbánirọ̀ tó fòkò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí Tinubu lọ rí LGI
Titi di asiko ti a n ko iroyin yii jọ, ajọ NYSC ko tii sọ nnkankan lori ọrọ naa.

Kókó èsì tí ìjọba àpapọ̀ sọ fún Amẹ́ríkà rèé lórí ẹ̀sùn tó fi kan Nàíjíríà pé ó ń pa ọ̀pọ̀ Kristẹni
Abọ iwadii ajọ kan, Observatory for Religious Freedom in Africa,sọ pe ida aadọrun-un (90%) awon Kristẹni ti wọn n pa kaakiri agbaye lọdun jẹ ọmọ Naijiria.

Ẹ fura o! Ìpínlẹ̀ Eko ló ń léwájú nínú àrùn Diphtheria, níbi tí èèyàn ogún ti kó o - NCDC
Atẹjade NCDC ni abọ iwadii arun naa lọsẹ kẹwaa foju han pe ogun eeyan (20) ni Diphtheria ti kọlu l'Ekoo.

Olubadan fojú hàn fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn ìròyìn tó ní ó ti wàjà
Ṣaaju ni iroyin ti kọkọ gbode pe Olubadan ti waja lẹyin aisan ranpẹ, ti iroyin naa si milẹ titi ni nnkan bii ọsẹ meji sẹyin.

Igbó ló máa ń fún mi ní ìmísí láti kọ ìtàn, mò ń mu igbó gan ni – Ijoba Lande
Ti ẹ ko ba gbagbe, ẹnu ọjọ mẹta yii ni Ijoba Lande bẹrẹ si n milẹ titi lori ayelujara lẹyin to fẹsun kan iyawo rẹ pe o ba ọkunrin mọkanlelogun ni ibalopọ.

"Mo ní ọmọ kan ṣoṣo, mo sì ti pàdánù rẹ̀ sínú ìjàmbá iná tó pa ọ̀dọ́ 59, kò sí ohun tí mò ń ṣe láyé mọ́"
Iroyin ni nnkan bii aago mẹta oru ni ina ọhun bẹrẹ lasiko ti ẹgbẹ akọrin takasufee, DNK n ṣere lọwọ, ina naa si jo titi di aarọ.

Ọlọ́pàá yìnbọn pa ara rẹ̀ lẹ́nu iṣẹ́, ariwo sọ
Àtẹ̀jáde ti agbẹnusọ ọlọ́pàá Ogun, Omolola Odutola fi léde ní Ajele Oloyede jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọlọ́pàá tó ń pèsè ààbò fún iléeṣẹ́ kan tó wà ní Igbesa, ìpínlẹ̀ Ogun.

Nọ́ọ̀sì tó gùn Mohbad ní abẹ̀rẹ̀ ṣàlàyé ohun tó wáyé fún Ilé ejọ̀
Ile ẹjọ ti sun igbẹjọ naa si ọjọ kọkanlelogun oṣu kẹta ọdun 2025.

Ìdí rèé tí a kò fi ní wọ́ Babangida lọ sílé ẹjọ́ lórí ikú bàbá mi - Ọmọ MKO
Ninu ifọrọwerọ kan to ṣe pẹlu ileeṣẹ iroyin abẹle, The Punch, Jamiu ni asiko fun iwadii nipa iku baba wọn ti kọja, ti ọpọ awọn eeyan to mọ nipa ohun to waye ni ọjọ Kejila oṣu Kẹfa ti jade laye.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

Ìjọba àná l'Osun gba owóyàá ogún mílíọ̀nù Dọ́la láti kọ́ ibùdó ìwòsàn alábọ́dé àmọ́ wọn kò ṣe é - Adeleke
BBC Yorùbá bá gómìnà ìpínlẹ̀ Osun, Ademola Adeleke sọ̀rọ̀, tó sọ ọ̀pọ̀ aṣeyọrí rẹ̀ áàrin ọdún mẹ́ta, àwọn tó ń darí ìjọba Osun, ọ̀rọ̀ bàbá ìsàlẹ̀, ipò ìlera àti bó ṣe máa ń jó.

Ọkùnrin tí ìdá 95% ojú rẹ̀ jẹ́ kìkì irun gba àmì ẹ̀yẹ
Patidar sọ pe awọn akẹgbẹ oun nile ẹkọ ko kọkọ tẹwọ gba oun amọ wọn pada ri oun gẹgẹ bii ọkan lara wọn bo tilẹ jẹ pe oun yatọ.

Ìjì líle kọlu Amẹrika, èèyàn 34 pàdánù ẹ̀mí wọn
Ni Kansas, eeyan mẹjọ lo ku nigba ti ọkọ bii marunlelaadọta kọlu ara wọn nitori afẹfẹ to gba igboro kan.

Taa ló gbé Abdulrahman, afurasí tí wọ́n bá òkú Yetunde nílé rẹ̀ n'Ilorin kúrò l'ẹ́wọ̀n tó wà? Ohun tí a mọ̀ rèé
Ohun ti a ri gbọ ni pe ọjọbọ ọsẹ yii ni wọn gbe Abdurahman Muhammadu Bello kuro lọgba ẹwọn naa, ti a ko si ti le sọ ibi ti wọn gbe lọ pato.

Ijọba Iran ń lo ìmọ̀ ẹ̀rọ láti mú àwọn obìnrin tó kọ̀ láti lo Hijab
Ẹrọ "drone" ni ijọba naa fi n ṣọ awọn obinrin ti ko ba lo hijab, bẹẹ ni wọn tun gbe aapu kan kalẹ ti araalu le maa lo lati fi ọrọ awọn obinrin to ba kọ lati lo hijab to ijọba leti.

Ọmọ mi ni ìrètí mi, ṣùgbọ́n wọn ò jẹ́ kó sanjọ́ - Ìyá Mojisola Awesu
Iya yi sọ eyi fun BBC News Yoruba ni ile ẹjọ giga kan ni Ilorin olu ilu ipinlẹ Kwara lẹyin igbẹjọ lori iku ọmọ rẹ.

Àwọn aṣòfin buwọ́lu owó orí tuntun, àti bí àwọn ìjọba yóò ṣe máa pín-in
Lapapọ, atunṣe mọkandinlogun (19) lo ni o waye, titi de ori eyi ti awọn gomina kan lawọn ko fẹ ko ri bẹẹ lapa Ariwa, ṣugbọn ti Aarẹ Tinubu sọ pe ilana to daa ju niyẹn.

BBC ṣe ìwádìí ẹ̀sùn pé àwọn ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ ń pa àwọn ọ̀dọ́ nípakúpa ní Congo
Awọn ọmọ ogun ólọtẹ M23 n daamu awọn araalu, wọn n fipa ko wọn sinu iṣẹ ologun, iku oro ni wọn fi n pa awọn ọdọ bayii, gẹgẹ bi iwadii ti BBC ṣe.

Kehinde Subair, ọmọ ilé ìgbìmọ̀-aṣòfin Oyo tẹ́lẹ̀ jáde láyé
Iroyin to tẹ wa lọwọ ni Subair jade laye niluu London ni aṣalẹ ọjọbọ, Ọjọ kẹtala oṣu kẹta ọdun 2025.

Mọ̀ nípa àṣà Gada níbi tí kábíèsí kìí tí lò ju ọdún mẹ́jọ lọ
Ọ̀pọ̀ èèyàn péjọ láti kópa níbi ayẹyẹ yíyan Abbaa Gadaa ní ẹkùn gúúsù Ethiopia.

Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Greenbook, áàpù tí NAFDAC ṣe láti fi dá ayédèrú oògùn mọ̀
Áàpù Greenbook náà yóò jẹ́ ojúnà láti gbógunti àwọn tó máa ń pèsè ayédèrú oògùn ní Nàìjíríà, tí yóò sì ṣe ìrànwọ́ fáwọn tó ń ra oògùn.

Ọwọ́ tẹ pásítọ̀ àti àwọn èèyàn mìí lórí ikú akẹ́kọ̀ọ́ LASU l'Ekoo
Igbesẹ oku hihu yii waye lẹyin ti ijọba ti kọkọ ti ṣọọṣi Sẹlẹ kan, Ileri Oluwa Parish, ti wọn ni ọmọkunrin naa ku si, pa.

Ilé ẹjọ́ fún Oriyomi Hamzat àti olorì Naomi ní ọ̀nà àbáyọ láti tètè yanjú ìgbẹ́jọ́ wọn
Ti ẹ ko ba gbagbe ọmọde marundinlogoji lo ku nibi eto ti wọn gbe kalẹ lati ṣe iranwọ fun awọn to ku diẹ kaato fun lawujọ ni ipari ọdun 2024.

Wo àwọn ọ̀nà tí o lè fi dáàbò bo ara à rẹ lọ́wọ́ ooru àmújù tó gbòde
Àjọ NiMET sọ pé ooru yìí le fa àwọn ìpèníjà ìlera, tí wọ́n sì gba àwọn èèyàn níyànjú láti máa wà níbi tó bá tutù lásìkò yìí.

Ọkọ̀ akọ́wọ̀ọ́rìn Ààrẹ pa aráàlú, awakọ̀ sá lọ
Ọwọ ọlọpaa ti tẹ dẹrẹba ọkọ naa, ti wọn si tun ti gba baali rẹ pe ko ma lọ si ile.

Ọ̀rọ̀ Sunday Igboho àti ìjọba àpapọ̀ gba ọ̀nà míràn yọ; Igboho tún ẹjọ́ pè
Ọrọ ọjọ ti Sunday Igboho pe ijọba apapọ Naijiria lori bi awọn oṣiṣẹ alaabo DSS ṣe kọlu ile rẹ tun ti ba ibomiran yọ.

Àwọn ǹnkan tó le tètè ba kíndìnrín rẹ jẹ́ àti bí o ṣe le mọ̀ tó bá ti bàjẹ́
Bi o ṣe le mọ pe aisan n ṣe kindin rẹ

Wo ìdájọ́ ilé-ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ìbanilórúkọjẹ́ tí Mercy Chinwo fi kan VDM

Kókó ohun tí Peter Obi àti Gómìnà Bala Mohammed sọ nínú ìpàdé ìkọ̀kọ̀ tí wọ́n ṣe
Lẹ́yìn tí Peter Obi ti fìdí rẹmi sọ́wọ́ ààrẹ Bola Ahmed Tinubu níbi ètò ìdìbò ọdún 2023 níbi tó ti gbé ipò kẹta, Peter Obi kò sinmi láti máa ṣe àbẹ̀wò sáwọn èèkàn olóṣèlú káàkiri Nàìjíríà.

Njẹ́ o mọ̀ pé ìjọba kìí pa àwọn tílé ẹjọ́ bá dájọ́ ikú fún ní Naijiria? Ìdí rèé
Lábẹ́ ìwé òfin ìwà ọ̀daràn Nàìjíríà, ìwà ìpànìyàn, ìgbéṣùmọ̀mí, ìdigunjalè, ṣíṣe ìrànlọ́wọ́ fún ìpànìyàn lọ́nà àìtọ́, ìdìtẹ̀gbàjọba jẹ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ilé ẹjọ́ fi le gbé ìdájọ́ ikú kalẹ̀ fún ọ̀daràn.

Obìnrin tó fi ilé onílé ṣe ìdúpẹ́ ní ṣọ́ọ̀ṣì di èèrò ilé-ẹjọ́
Lẹyin ọjọ diẹ ti afurasi naa ṣe idupẹ irọ ni ṣọọṣi ni ẹni to ni ile gan-an, tako idupẹ naa.

Obìnrin kan déèrò ẹ̀wọ̀n lẹ́yìn tó sọ fún Jesu pé kó gé irun orí rẹ̀ lórí Tiktok
Igbẹjọ rẹ lo waye lẹyin ti oniruru ẹgbẹ awọn ọmọlẹyin Kristi kọwe ẹsun ọrọ odi mọ afurasi ọhun.

Ẹ̀mí ṣòfò, èèyàn mẹ́rin farapa, ọ̀pọ̀ dúkìá jóná nínú ìjàmbá iná lórí afárá Otedola l'Eko
Ileeṣẹ to n ri si iṣẹlẹ pajawiri l'Eko, LASEMA lo fidi iroyin naa mulẹ ninu atẹjade to fi ṣọwọ si awọn akọroyin.





We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always



This Section Can Accommodate Your Adverts





Charleans In Celebration Mode

We have put an assorted mix of pics here for your enjoyment. We are always hungry for more - so if you have taken or have access to some pics remotely related to our issue, please do not hesitate to send them to the web admin team

SCOBA PARTNERS

corporates and enterprise businesses we have the pleasure to connect with.